CELEBRATE PURITY AND TRUTH
THE SEED
“Let us celebrate our Passover, then, not with bread having the old yeast of sin and wickedness, but with the bread that has no yeast, the bread of purity and truth.” 1 Corinthians 5:8 (GNB)
The Passover experience signifies our crossing from sin into the righteousness of Christ. It is a call to live in purity and truth. Sadly, many decorate impurity with excuses, making sin appear acceptable. But God expects His children to celebrate their new life in Christ with sincerity and holiness. If you have truly embraced Jesus, old ways must give way to new life. Living in Christ means walking in integrity, fleeing sin, and shining as light in a dark world. Your transformation must be visible to those around you. Celebrate your redemption with a pure heart. Let your life reflect the truth of the gospel daily.
Reflection: True celebration of redemption is marked by purity and truth.
BIBLE READING: 2 Corinthians 5:14–17
PRAYER: Lord Jesus, help me to celebrate my new life in You with purity and truth, bringing glory to Your name. Amen.
Sunday, July 26, 2026
ṢE ÀJỌYỌ ÌWÀ MÍMỌ́ ATI ÒTÍTỌ́
IRUGBIN NAA:
“Nítorí náà, ẹ jẹ́ kí a ṣe àjọyọ náà, kì í ṣe pẹ̀lú ìwúkàrà àtijọ́ tàbí ìwúkàrà ìwà búburú, bí kò ṣe pẹ̀lú àìwúkàrà òtítọ́ àti ìwà mímọ́.” — 1 Kọ́ríńtì 5:8
Ìrírí Ìrékọjá ń tọ́ka sí ìrékọjá wa kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ sí òdodo Kristi. Ó jẹ́ ìpè sí ìgbésí ayé ìwà mímọ́ àti òtítọ́. Ó bà ní nínú jẹ́ pé ọ̀pọ̀ ènìyàn máa ń fi àwáwí ṣe ohun àìmọ́, tí wọ́n sì ń mú kí ẹ̀ṣẹ̀ dà bí ohun tí a lè fara mọ́. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run fẹ́ kí àwọn ọmọ Rẹ̀ ṣe àjọyọ ìgbésí ayé tuntun wọn nínú Kristi pẹ̀lú òtítọ́ àti ìwà mímọ́. Bí o bá ti gba Jesu nitõtọ́, àwọn ọ̀nà àtijọ́ gbọ́dọ̀ fi àyè sílẹ̀ fún ìgbésí ayé tuntun. Gbígbé nínú Kristi túmọ̀ sí rírìn nínú ìwà títọ́, sá fún ẹ̀ṣẹ̀, àti títàn bí ìmọ́lẹ̀ nínú ayé òkùnkùn. Ìyípadà rẹ gbọ́dọ̀ hàn sí àwọn tí ó wà ní àyíká rẹ. Jẹ́ kí ìgbésí ayé rẹ jẹ́ ẹ̀rí fún ìhìnrere lójoojúmọ́.
ÀṢÀRÒ: Àjọyọ ìrapada tòótọ́ ni a fi ìwà mímọ́ àti òtítọ́ hàn.
BIBLE READING: 2 Kọ́ríńtì 5:14–17
PRAYER: Jesu Oluwa, ràn mí lọ́wọ́ láti ṣe àjọyọ ìgbésí ayé tuntun nínú Rẹ pẹ̀lú ìwà mímọ́ àti òtítọ́, kí n lè mú ògo bá orúkọ Rẹ. Amin.